News
Sunday Ighoho: Odolaye Aremu Queries Gani Adams On His ‘Relevance’ In The Yoruba Nation
Sunday Ighoho: Odolaye Aremu Queries Gani Adams On His ‘Relevance’ In The Yoruba Nation
Dear Ààrẹ,
…and now that the citizens of Káàrọ́ọ̀-ojìíre, kings and the King Of Ìjẹ̀búland – Awujale had thrown their full weight behind OgunSunday Igboho, I wonder what assignment would fall on you now our dear Bishop Ààrẹ Ona Kakanfo in the unfolding saga. I am totally lost at really figuring out your relevance in the present disposition. I mean of what strategic purpose are you at the present time? Or is it part of the conceived strategy, Bishop that you would preemptively lead the defense from the nearest C&S Ayọ̀ Ní O Headquarters or from any of its branches or from the sanctum of your bedroom?
Rádaràda! Wòlíì Lógun Ọfẹ, ẹ jẹ gbétìjú tí, kẹẹ tú àmùrè wèrè kẹẹ jọ́ìnì àwọn ọmọ ogún Sunday! Láìkú Ẹ̀gìrì, awọ wèrè yin tí ndun bíi ìlú o! Èmi o kúkú rí Dúdúbíaró báwí bí ò ṣ’Abélépopọ́n tó fi joyè tí ò méékí sẹ́ẹ̀nsì. Ẹni ó yẹ kí wọ́n ó fi j’ẹmẹsẹ̀ ààfin ti wọn fi j’ààrẹ Ọ̀nà Kakanfòò! Tani o ṣàìmọ̀ wípé èèrà yín tí gbe’hun ó ju ni? Ẹrú to pá Ogunmola Ibadan. Ẹrú to pá Kurunmi Ijaye. Ẹrú tó pá Akintola Ogbomoso. Ẹrú to pá Abiola Gbagura. Ẹrú ọ̀hún lẹ́yìn tẹ́rí sí laarin ọ̀sẹ̀ kan un t’ọ́rùn yín tí sáré súnkì un, to ti ń wọ̀yìn yí un! Àwọn ẹni à bá tà ká fi ràtùpà. Isshhh. Ká tó wí, ká tó fọ̀, wọn ò mọ f’owo r’oyè kiri àdúgbò! Wèrè tí wọn ò le fi jẹ Kọ́bùrù lasan ń Dagbolu! Shiọọ! Ọ̀lẹ òsì! Kìkì orí lásán ni wọn ń sanra sí lojoojumọ bí oko ẹṣin!
Gẹ́gẹ́bí ìṣe mi, pàápàá julọ f’ẹyin wèrè tẹ́ẹ tó bẹrẹ sí níí bu mi wípé: “pẹ́pẹ́sẹ́ ó, Odolaye o ni rẹspẹk kan bayi laa, àti wípé gbogbo àwọn àgbà Yoòbá-Ronú ni wèrè yí nbu káàkiri ìlú!” Irọ́ ni ó! Bẹ́ẹ̀kọ́ lọ̀rọ̀ ri ó! Wàlahi orí ìdọ̀bálẹ̀ẹ nàtẹ́ẹ́rẹ́ ni mo wá nigba mo kọ lẹ́tà were yí o! Tọ̀wọ̀tọ̀wọ̀ ni mo si fi kọọ́ pẹ̀lú! Èmi ni tiyín ni tòótọ́. Ọmọlúwàbí pàtàkì, ọmọlúwàbí tòótọ́ – láti Fiditi, Dagbolu, Gárééjí-Olúọ́dẹ títí tó fi d’alujanna ile Anabi! Tí lẹta yí bá bọ́ s’ódì araa yín, tínú bíi yín gaan, ẹ dakun ẹ gbe rẹkọọdu tuntun wèrè Wasiu síi. Ẹ farabalẹ̀ gbọ́ọ. Kẹ́ẹ sì méékí ṣuọ̀ wípé: “Ẹ Yọ́nú Sími” síríọ́slì!
Odolaye Bàá Waki Aremu
Òpópónà kẹtàlá, ojúlé kejì
Àdúgbo Káwọ́ọ̀dù-L’ààrẹ
Gárééjí-Olúọ́dẹ
Ọ̀yọ́ Aláàfin
Ńbì tí Ọba wá Alayeluwa Abélépopọ́n ti ń f’awon were joyè
- Top Stories12 hours ago
We will no longer allow obstruction of our operations after Ododo interfered in Yahaya Bello’s attempted arrest – EFCC
- News11 hours ago
Iyalode Line Visits Olubadan Designate
- News9 hours ago
Black Market Dollar (USD) To Naira (NGN) Exchange Rate Today 18th April 2024
- Top Stories12 hours ago
EFCC: Why Yahaya Bello Can’t Evade Arrest, Prosecution — Falana
- Top Stories6 hours ago
Breaking: Police Apologizes Over Reports Of DJ Switch’s Arrest
- Politics11 hours ago
FIRS Chairman Releases Statement As Tinubu Inaugurates National Single Window Committee
- News5 hours ago
Heritage Bank In Crisis…Shut Down Over Mass Sack, Undue Process
- Entertainment12 hours ago
Bobrisky Reportedly Moved From Ikoyi To Kirkiri Prison